Ṣe ni ọrọ tun gba ọna mii-ii yọ lori ati yan Olubadan tuntun fun ilu Ibadan, Ọba Owolabi Ọlakulẹhin, nigba ti Ọtun Olubadan, to tun jẹ gomina tẹlẹ nipinlẹ Ọyọ,Oloye Raṣidi Ladọja atawọn afọbajẹ yooku kuna lati kọwọ bọwe adehun lati yanju igbesẹ ọlọbade.
O sọ pe “ Emi pẹlu awọn igbimọ Olubadan ti jọ jokoo papọ, a si ti sọrọ, a si ti gba lati gbe ẹjọ kuro ni kootu.“Mo gbọ pe wọn ti bẹrẹ si nii kọwọ bọwe adehun, lẹyin ti gbogbo wọn ba ṣetan,emi naa yoo waa kọwọ bọwe ni ọna ọdọ mi, bilẹ ọjọ keji ba si ti n mọ, a n lọ si kootu lati lọọ pe ẹjọ pe a o ṣe mọ.
Lara awọn ti wọn wa nibi ipade to waye ni afin Olubadan ni Ọja’ba ni Osi Balogun, Ọba Lateef Gbadamọsi Adebimpe; Aṣipa Olubadan, Ọba Abiọdun Kọla-Daisi; Aṣipa Balogun, Kọla Adegbọla; Ẹkẹrin Balogun, Ọba John Isioye-Dada ati Ẹkaarun Olubadan, Ọba Adebayọ Akande.
Nigeria Latest News, Nigeria Headlines
Similar News:You can also read news stories similar to this one that we have collected from other news sources.
Source: TheNationNews - 🏆 6. / 69 Read more »
Source: GuardianNigeria - 🏆 1. / 94 Read more »
Source: DailyPostNGR - 🏆 11. / 59 Read more »
Source: TheNationNews - 🏆 6. / 69 Read more »
Source: TheNationNews - 🏆 6. / 69 Read more »
Source: TheNationNews - 🏆 6. / 69 Read more »